Adúmáadán Black and Beautiful

Adúmáadán

Bí a bá mú egbin kúrò láwùjọ ẹranko
Ẹranko tó dára ti tán
Bí a bá mú òdú kúrò láwùjọ ẹ̀fọ́
Ẹ̀fọ́ tó dára tó jọjú ti dínkù
Ẹni tó fọ́jú mẹwà egbin bí ó bá fọwọ́ pa á lára
Àńbọ̀sìbọ́sí ẹni tó lẹ́yinjú méjèèjì
Adúmáadán obìnrin ló múmi rántí
Ẹranko tó wuyì láwùjọ ẹranko
Dúdúparíọlá olólùfẹ́ ló múmi dárúkọ òdú láwùjọ ẹ̀fọ́
Ó dúdú ó rì rébété
Eyín funfun nígínnígín
Ètè ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ló sì bo gbogbo wọn
Bójú bá ti pàdé lojú ń rinjú
Bí n bá ti wò ẹ́ ni mò ń yin Yáárábì nísàlú-ọ̀run
Ìfẹ́ mú mi títí
Ojú ń ro mí
Mo ń dá rẹ́rìn-ín nígbà gbogbo
Báráyé bá bi mi pé kí ló dé
Gorodóòmù ìfẹ́ adúmáadán ló démi mọ́lẹ̀ pirigidi.
 

Original Poem by

Taiwo Olunlade

Translated by

Tọ́lá Ọ̀ṣunnúgà with The Poetry Translation Workshop Language

Yoruba

Country

Nigeria